Báwo ni ìbá ṣe dùn tó, ẹ̀yin Ọmọ Igbó-Ọrà, tí ó bá jẹ́ pé ní àkókò tí ó ti yẹ kí a lọ pàdé ìjọba-Adelé Orílẹ̀-Èdè Olómìnira Tiwantiwa ti Yorùbá (Democratic Republic of the Yoruba, D.R.Y) ní ìlú Ìbàdàn, ní ọjọ́ kẹ́tàláá sí ìkẹ́rindín lógún oṣù igbe ẹgbàá-ọdún ó lé mẹ́rinlélógún yí, ni gbogbo wa ti ṣe bẹ́ẹ̀, ṣùgbọ́n ó bà ni, kòì tíì bàjẹ́; ṣùgbọ́n tó bá jẹ́ pé a ti bọ́ síta níjọ náà ni, kí ìjọba Adelé wa ti wọ’nú oríkò ilé-iṣẹ́ ìjọba, ayẹyẹ àwọn Ìbejì ti ọdún yí ní Igbó-Ọrà ìbá jẹ́ ohun mánigbàgbé.

Ìròyìn tí a gbọ́ sọ pé oṣù-ọ̀wàrà yí ni ọdún àwọn Ìbejì ní ìlú Igbó-Ọrà, Democratic Republic of the Yoruba, tí Igbó-Ọrà sì jẹ ibi tí a gbọ́ pé ọ̀pọ̀ ènìyàn rí wọn gẹ́gẹ́bí ibi tí Ìbejì pọ̀jù sí ní Àgbáyé.

A ní ìrètí àti ìdùnnú pé láìpẹ́ yí ni Olódùmarè máa ṣí’dí ajẹgàba Nàìjíríà àti àwọn ẹmẹwà rẹ gbogbo kúrò ní ilẹ̀ Yorùbá; nígbànáà ni ayẹyẹ àwọn Ìbejì ní Igbó-Ọrà kò ní jẹ́ tí ebi tàbí ìnira, nítorí ìjọba Adelé Orílẹ̀-Èdè Yorùbá yíò ti wà nínú oríkò ilé-iṣẹ́ ìjọba wa gbogbo.

Ìwọ tí o pera rẹ ní gómìnà, o ò kì nṣe gómìnà D.R.Y o, ilẹ̀ D.R.Y sì ni Igbó-Ọra àti gbogbo Ìpínlẹ̀ Ìbàdàn wà (èyí tí ó njẹ́ Ìpínlẹ̀ Ọyọ́ nígbàti Democratic Republic of the Yoruba kòì tíì dá dúró kúrò nínú Nàìjíríà). Nítorí náà kúrò ní ilé-iṣẹ́ ìjọba tí o jẹgàba sí: láìpẹ́ láìjìnà, o máa ṣẹ̀sín jáde náà ni.

Gbogbo ọmọ Igbó-Ọrà, ẹ gbárùkù ti Orílẹ̀-Èdè wa, Orílẹ̀-Èdè Olómìnira Tiwantiwa ti Yorùbá, ẹ mọ̀, dájú, pé a ti kúrò nínú Nàìjíríà ní ogúnjọ́ oṣù bélú ẹgbàá-ọdún ó lé méjìlélógún, a sì ti bẹ̀rẹ̀ ìjọba wa ní ọjọ́ kéjìlá oṣù igbe ẹgbàá-ọdún ó lé mẹ́rinlélógún.

The Democratic Republic of the Yoruba also known in the Yoruba history as Yoruba Nation, Yoruba Kingdom, Yoruba Land and Yoruba Country is the newest nation in the world. The 55th nation in Africa and 17th in Western Africa as of 12th April 2024. Yoruba is know a sovereign nation and its no longer part of Nigeria.